languageIcon
search
search
brightness_1 Sísọ ìrántí Ọlọ́hun, èyí tí ẹ̀gbàwá wà fún, nígbà tí a bá fẹ́ wọ ààyè ẹ̀gbin àti nígbà tí a bá fẹ́ jade kúrò níbẹ̀

Wọ́n ṣe é ní Sunnah fún ẹni tó bá fẹ́ wọ ààyè ẹ̀gbin, kí ó sọ ohun tó wá nínú Ṣaḥīḥu méjèèjì:

’Anas – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà á wá pé: “Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – nígbà tó bá fẹ́ wọ ààyè ẹ̀gbin máa ń sọ pé: “Allāhumma ’innī ’a‘ūdhu bika minal-khubuthi wal-khabā’ith (Ìrẹ Ọlọ́hun! Dájúdájú èmi ń wá ìṣọ́ pẹ̀lú Rẹ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọkùnrin àti àwọn obìnrin èṣù)”. Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (6322), Muslim gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (375).

(Al-Khubuth) pẹ̀lú fífún háràfí ni ẹ̀wọ́ ḍammah ni: Àwọn ọkùnrin èṣù, nígbà tí al-khabā’ith jẹ́ àwọn obìnrin wọn. A jẹ́ wí pé èyí yóò jẹ́ wíwá ìṣọ́ kúrò lọ́dọ̀ àwọn ọkùnrin àwọn èṣù àti àwọn obìnrin wọn .

(Al-Khubth) pẹ̀lú fífún háràfí ni ẹ̀wọ́ sukūn  ni: Aburú, nígbà tí al-khabā’ith jẹ́ àwọn ẹ̀mí burúkú. A jẹ́ wí pé èyí yóò jẹ́ wíwá ìṣọ́ kúrò níbi aburú àti àwọn tó máa ń ṣe é. Fífún un ní sukūn ni ó kún jùlọ.  

Wọ́n ṣe é ní Sunnah fún ẹni tó fẹ́ jáde kúrò ní ààyè ẹ̀gbin kí ó sọ:

Ohun tó wá nínú Musnad Aḥmad, Sunan Abī Dāwūd àti ti At-Tirmidhī, Al-Albānī kà á sí ẹ̀gbàwá tí ó ní àlááfíà: Láti ọ̀dọ̀ ‘Ā’ishah – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i –, ó sọ wí pé: “Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – nígbà tó bá fẹ́ jáde kúrò ní ààyè ẹ̀gbin máa ń sọ pé: “Ghufrānak (Mò ń tọrọ àforíjìn Rẹ̀)”. Aḥmad gbà á wà pẹ̀lú òǹkà (25220), Abū Dāwūd gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (30), At-Tirmidhī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (7), Al-Albānī kà á sí ẹ̀gbàwá tí ó ní àlááfíà nínú (Taḥqīqu Mishkātil-Maṣābīḥ 1/116).

 

brightness_1 Wọ́n ṣe kíkọ àsọtẹ́lẹ̀ sílẹ̀ ní Sunnah

Kíkọ àsọtẹ́lẹ̀ sílẹ̀, Sunnah ni fún gbogbo Mùsùlùmí, nígbà tó bá ń ṣe àìsàn, tàbí ó wà ní àlááfíà, nítorí ọ̀rọ̀ tí Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a sọ pé: “Kò ní ẹ̀tọ́ fún èèyàn tó jẹ́ Mùsùlùmí, tó ní nǹkankan tí ó yẹ kí ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa rẹ̀, kí ó sùn fún òru ọjọ́ méjì àyàfi kí àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀”. Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (2783), Muslim gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (1626). Nínú ḤadīthIbn ‘Umar – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí àwọn méjèèjì – gbà wá. Sísọ òru ọjọ́ méjì nínú Ḥadīth yìí, kì í ṣe láti fi ààlà sí i. Ṣùgbọ́n ohun tí wọ́n gbà lérò ni kí àsìkò kékeré kankan má rékọjá pẹ̀lú rẹ̀, àyàfi kí àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ wà ní kíkọ́ sílẹ̀ ní ọ̀dọ̀ rẹ̀, nítorí pé kò mọ ìgbàwo ni yóò kú, èyí jẹ́ Sunnah tó kárí gbogbo èèyàn.

Ṣùgbọ́n kíkọ́ àsọtẹ́lẹ̀ nípa ohun tó wà lọ́rùn rẹ̀ nínú àwọn iwọ̀ Ọlọ́hun – Ọba tí Ọlá Rẹ̀ ga –, bí Zakāh yíyọ, Ḥajj ṣíṣe, sísan ìtanràn, tàbí àwọn iwọ̀ àwọn èèyàn bíi gbèsè àti dída àwọn nǹkan gbà-fi-pamọ́ padà, ọ̀ranyàn ni èyí, kì í ṣe Sunnah, nítorí pé sísan àwọn iwọ̀ tó jẹ́ ọ̀ranyàn so mọ́ ọn, pàápàá jùlọ tí ẹni kankan (lẹ́yìn rẹ̀) kò bá mọ̀ nípa àwọn iwọ̀ yìí [ohun tí ohun tó jẹ́ ọ̀ranyàn kò le pé àyàfi pẹ̀lú rẹ̀, ọ̀ranyàn ni òun náà] .

 

brightness_1 Mímáa retí ìrun

Mímáa retí ìrun jẹ́ ara Sunnah tí ọlá tó tóbi wà lórí rẹ̀ .

Ẹ̀rí rẹ̀ ni :

Ḥadīth tí Abū Hurayrah – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá, ó sọ wí pé: Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – sọ wí pé: “Ẹni kẹ́ni nínú yín kò ní yé máa bẹ lórí ìrun, ní òpin ìgbà tó bá jẹ́ wí pé ìrun ni ó ń dá a dúró, tí kò sí ohun tó kọ̀ fún un láti padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ará ilé rẹ̀ bíkòṣe ìrun”. Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (659), Muslim gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (649). Pẹ̀lú mímáa retí ìrun, yóò máa gba ẹ̀san ìrun kíkí.

Abū Hurayrah – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà á wá pé: Dájúdájú  Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – sọ wí pé: “Àwọn Malā’ikah yóò máa ṣe àdúà fún ẹni kẹ́ni nínú yín, ní òpin ìgbà tó bá sì wà níbi tó ti kírun, tí kò bá ti ṣe ẹ̀gbin níbẹ̀. Ìrẹ Ọlọ́hun! Ṣe àforíjìn fún un. Ìrẹ Ọlọ́hun! Kẹ́ ẹ́. Àti pé ẹni kẹ́ni nínú yín kò ní yé máa bẹ lórí ìrun, ní òpin ìgbà tó bá jẹ́ wí pé ìrun ni ó ń dá a dúró, tí kò sí ohun tó kọ̀ fún un láti padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ará ilé rẹ̀ bíkòṣe ìrun”. Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (659), Muslim gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (649). Ọ̀rọ̀ tó sọ pé: “Tí kò bá ti ṣe ẹ̀gbin níbẹ̀” túmọ̀ sí: Ní òpin ìgbà tí kò bá ti ṣe ohun tí yóò ba àlùwàlá rẹ̀ jẹ́. Ó tún wá ní ọ̀dọ̀ Muslim pé:

Ní òpin ìgbà tí kò bá ti ṣe ẹnì kankan ní ṣùtá níbẹ̀, tí kò sì ṣe ẹ̀gbin níbẹ̀”. Muslim gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (649). Ìtumọ̀ èyí ni pé: Májẹ̀mu ẹ̀san dáadáa yìí ni kí ó má fi ṣùtá kan ẹnì kankan níbi tó jókòó sí, kí àlùwàlá rẹ̀ sì má jà á.