languageIcon
search
search
brightness_1 Nínú Sunnah ni kí á bẹ̀rẹ̀ bàtà wíwọ̀ pẹ̀lú ẹsẹ̀ ọ̀tún

Nínú Sunnah, nígbà tí Mùsùlùmí bá fẹ́ wọ bàtà ẹsẹ̀ rẹ̀ méjèèjì, ni kí ó bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú ẹsẹ̀ ọ̀tún. Nínú Sunnah, nígbà tí ó bá fẹ́ bọ́ bàtà ẹsẹ̀ rẹ̀ méjèèjì, ni kí ó bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú ẹsẹ̀ òsì.

Ẹ̀rí rẹ̀ ni : Nítorí Ḥadīth tí Abū Hurayrah – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá, ó sọ wí pé: Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – sọ wí pé: “Nígbà tí ẹni kẹ́ni nínú yín bá fẹ́ wọ bàtà, kí ó bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú ẹsẹ̀ ọ̀tún, nígbà tó bá fẹ́ bọ́ ọ, kí ó bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú ẹsẹ̀ òsì. Ẹsẹ̀ ọ̀tún ni ó gbọdọ̀ jẹ́ àkọ́kọ́ tí a ó wọ̀ nínú ẹsẹ̀ méjèèjì, òun ni ó sì gbọdọ̀ jẹ́ èyí tí a ó bọ́ gbẹ̀yìn nínú àwọn méjèèjì”. Al-Bukhārī  gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (5856).  

Nínú ẹ̀gbàwá mìíràn ti Mùslim gbà wá: “Ẹni kẹ́ni nínú yín kò gbọdọ̀ máa rìn pẹ̀lú bàtà ẹsẹ̀ kan. Kí ó wọ méjèèjì papọ̀ tàbí kí bọ́ àwọn méjèèjì lápapọ̀”. Muslim gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (2097).

Sunnah mẹ́ta wà nínú Ḥadīth méjèèjì yìí:

1. Kí á máa bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú ẹsẹ̀ ọ̀tún, nígbà tí a bá fẹ́ wọ̀ bàtà.

2. Kí á máa bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú ẹsẹ̀ òsì, nígbà tí a bá fẹ́ bọ́ bàtà.

3. Kí á máa wọ bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì papọ̀, tàbí kí á bọ́ méjèèjì lápapọ̀, kí á má baà máa rìn pẹ̀lú bàtà ẹsẹ̀ kan.

brightness_1 Nínú Sunnah ni mímáa lo lọ́fínńdà

Nítorí Ḥadīth tí ’Anas – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá, ó sọ wí pé: Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – sọ wí pé: “Nínú gbogbo ohun tí ń bẹ láyé, wọ́n fi ìfẹ́ àwọn obìnrin àti lọ́fínńdà sími lọ́kàn, wọ́n sì fi ìtutù ojú mi síbi ìrun kíkí”. Aḥmad gbà á wà pẹ̀lú òǹkà (12293), An-Nasā’ī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (3940),  Al-Albānī, nínú Ṣaḥīḥun- Nasā’ī, sọ wí pé: “Ó jẹ́ Ḥadīth tí ó dára, tí ó sì ní àlááfìà”.

Ṣùgbọ́n sísọ ẹ̀gbàwá yìí pẹ̀lú gbólóhùn: “Wọ́n fi ìfẹ́ nǹkan mẹ́ta sí mi lọ́kàn nínú ilé ayé yín yìí”, jẹ́ ohun tó lẹ.

– Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – máa ń kórìíra kí wọ́n máa rí òórùn burúkú lára rẹ̀: Dájúdájú ó wá, lọ́dọ̀ Al-Bukhārī, nínú Ḥadīth tó gùn, láti ọ̀dọ̀ ‘Ā’ishah – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i –, ó sọ pé:  “Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – jẹ́ ẹni tí ó máa ń le lára rẹ̀ kí wọ́n rí òórùn burukú lára rẹ̀”. Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (6872), ìtumọ̀ èyí ni òórùn tí kó dára.

Wọ́n kórìíra dídá lọ́fínńdà padà.

Nítorí Ḥadīth tí ’Anas – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá pé: “Dájúdájú Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – kì í dá lọ́fínńdà padà”.  Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (2582).