languageIcon
search
search
beforeFajronColorIcon Àwọn Sunnah tí kò ní àsìkò/ Lílọ sí Mọṣáláṣí/ ( Iye òǹkà òpó-ìrun (rak‘ah) rẹ̀ 8 Àwọn Sunnah )
brightness_1 Kí ó jáde kúrò ní ilé rẹ̀ ní ẹni tí ó mọ́; nítorí kí wọ́n le máa kọ ẹ̀san rere fún un lórí àwọn ìgbésẹ̀

Nítorí Ḥadīth Abū Hurayrah – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá pé; dájúdájú Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – sọ wí pé: “Ìrun ọkùnrin, pẹ̀lú àkójọpọ̀ àwọn Mùsùlùmí, yóò lékún ju ìrun tí ó kí nínú ilé rẹ̀ àti ní ọjá rẹ̀  lọ, ní ìlọ́po ogún lé díẹ̀, èyí rí bẹ́ẹ̀ nítorí pé tí ẹni kẹ́ni nínú wọn bá ṣe àlùwàlá, tí ó sì ṣe àlúwàlá rẹ̀ dáadáa, lẹ́yìn náà tí ó wá sí Mọṣáláṣí, tí ohun kankan kò gbé e dìde bíkòṣe ìrun, tí kò gba nǹkankan lérò bíkòṣe ìrun, kò ní gbé ìgbésẹ̀ kan àyàfi kí wọ́n fi gbé ipò rẹ̀ ga, kí wọ́n sì fi pa ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ kan rẹ́ títí tí yóò fi wọ Mọṣáláṣí. Nígbà tí ó bá wọ Mọṣáláṣí tán, yóò máa gba ẹ̀san ẹni tí ó wà lórí ìrun, ní òpin ìgbà tí ó bá ti jẹ́ wí pé ìrun ni ó ń dá a dúró. Àti wí pé àwọn Malā’ikah yóò máa tọrọ ìkẹ́ àti ìgẹ́ Ọlọ́hun fún ẹni kẹ́ni nínú yín, ní òpin ìgbà tí ó bá sì wà ní ibùjokòó rẹ̀ tí ó ti kírun. Wọn yóò máa wí pé: Ìrẹ Ọlọ́hun! Kẹ́ ẹ. Ìrẹ Ọlọ́hun! Ṣe àforíjìn fún un. Ìrẹ Ọlọ́hun! Gba ìrònúpìwàdà rẹ̀. Ní òpin ìgbà tí kò bá ti ṣe ẹnìkankan ní ṣùtá níbẹ̀, ní òpin ìgbà tí kò bá ti ṣe ẹ̀gbin níbẹ̀” Muslim gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (649).

brightness_1 Kí ó kírun òpó-méjì láti fi kí Mọṣáláṣí

Èyí yóò wáyé, tí ó bá jẹ́ wí pé ó tètè wá kírun, dájúdájú wọ́n ṣe é ní Sunnah fún un kí ó má jókòó títí tí yóò fi kí òpó-ìrun méjì. Nítorí Ḥadīth tí Abū Qatādah – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá, dájúdájú ó sọ wí pé: Ḥumayd tàbí Abū Usayd gbà wá, ó sọ wí pé: Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – sọ wí pé: “ẹni kẹ́ni nínú yín bá wọ Mọṣáláṣí, kò gbọdọ̀ jókòó títí tí yóò fi kí òpó-ìrun méjì”.  Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (1163), Muslim sì gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (714).

Ìrun Sunnah tí a máa ń kí síwájú ìrun ọ̀ranyàn, tí to láti dípo ìrun tí a fi máa ń kí Mọṣáláṣí, tí ó bá jẹ́ ìrun ọ̀ranyàn tí ó ní ìrun Sunnah tí a máa ń kí síwájú rẹ̀, bíi ìrun àfẹ̀rẹ̀mọ́júmọ́ àti ìrun ọ̀sán, tàbí ìrun Sunnah tí a máa ń kí ní àsìkò ìyálẹ̀ta, tí ó bá wọ Mọṣáláṣí ní àsìkò ìyálẹ̀ta, tàbí ìrun Witr, tí ó bá jẹ́ wí pé ó kí i ní Mọṣáláṣí, tàbí ìrun ọ̀ranyàn, nítorí pé ohun tí wọ́n gbà lérò pẹ̀lú kíkí Mọṣáláṣí ni: Kí ó má jókòó títí tí yóò fi kírun. Nítorí ohun tí ó wà nínú rẹ̀, nínú mímáa gbé àwọn Mọṣáláṣí ró pẹ̀lú ìrun kíkí, nítorí kí ó má ṣe máa wá síbẹ̀ láìkírun kankan.

brightness_1 Sunnah ni ó jẹ́ fún àwọn ọkùnrin kí wọ́n máa yára wá sí sááfú àkọ́kọ́

Sunnah ni ó jẹ́ fún àwọn ọkùnrin kí wọ́n máa yára wá sí sááfú àkọ́kọ́, ohun ní ó lọ́lá jùlọ nínú àwọn sááfú, ṣùgbọ́n fún àwọn obìnrin, èyí tí ó lọ́lá jùlọ nínú rẹ̀ ni èyí tí ó bá gbẹ̀yìn nínú rẹ̀.

Nítorí Ḥadīth tí Abū Hurayrah – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá pé; dájúdájú Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – sọ wí pé: “Èyí tí ó lóore jùlọ nínú sááfú àwọn ọkùnrin ni àkọ́kọ́ rẹ̀, èyí tí ó burú jùlọ nínú rẹ̀ ni ìgbẹ̀yìn rẹ̀, ṣùgbọ́n èyí tí ó lóore jùlọ nínú sááfú àwọn obìnrin ni ìgbẹ̀yìn rẹ̀,  èyí tí ó burú jùlọ nínú rẹ̀ ni àkọ́kọ́ rẹ̀” Muslim sì gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (440). Ìtumọ̀ pé òhun ni ó lóore jùlọ ni pé: Òhun ní ẹ̀san rere àti ọlá rẹ̀ pọ̀ jùlọ. Ìtumọ̀ pé òhun ni ó burú jùlọ ni pé: Òhun ní ẹ̀san rere àti ọlá rẹ̀ kéré jùlọ. 

Ḥadīth yìí wà fún ìgbà tí àwọn ọkùnrin àti àwọn obìnrin bá kírun papọ̀, tí kò sì sí gàgá kankan, bóyá ògiri ni tàbí ohun tí ó jọ ọ́, láàrin wọn. Nígbà náà èyí tí ó lóore jùlọ nínú sááfú àwọn obìnrin ni ìgbẹ̀yìn rẹ̀, nítorí pé dájúdájú ohun ní ó fi wọ́n pamọ́ jùlọ kúrò níbi kí àwọn ọkùnrin máa wò wọ́n. Ṣùgbọ́n tí ó bá jẹ́ pé gàgá, bóyá ògiri ni tàbí ohun tí ó jọ ọ́, wà láàrin wọn, tàbí gẹ́gẹ́ bí ò ti wà níbi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn Mọṣáláṣí wa, ní ayé òde-òní, pẹ̀lú pé wọ́n ṣẹ̀ṣà ààyè ìkírun tí ó dá wà fún àwọn obìnrin nìkan, nínú irú ìṣesí báyìí, èyí tí yóò lọ́lá jùlọ nínú sááfú àwọn obìnrin ni àkọ́kọ́ rẹ̀, nítorí pé ohun tí ó le fa kí wọ́n súnmọ́ àwọn ọkùnrin kò sí mọ́, nítorí pé ìdájọ́ máa ń rìn pẹ̀lú ìdí rẹ̀, bóyá ó ń bẹ ni tàbí kò sí. Àti nítorí ẹ̀rí gbogboogbò tí ó wá lórí lílọ́lá sááfú àkọ́kọ́ nínú àwọn Ḥadīth kan, nínú rẹ̀ ni:

Ḥadīth tí Abū Hurayrah – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá pé dájúdájú Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – sọ wí pé: “Tí ó bá jẹ́ wí pé àwọn èèyàn mọ ohun tí ń bẹ níbi ìrun pípè àti sááfú àkọ́kọ́ (nínú ọlá) ni, lẹ́yìn náà tí wọn kò rí ọ̀nà débẹ̀ àyàfi pẹ̀lú kí wọ́n muje, dájúdájú wọn ì bá muje. Tí ó bá sì jẹ́ wí pé wọ́n mọ ohun tí ń bẹ nínú mímáa tètè yára lọ sí Mọṣáláṣí (nínú oore) ni, dájúdájú wọn kò bá gbìyànjú láti gbawájú mọ́ ara wọn lọ́wọ́ lọ síbẹ̀. Tí ó bá sì jẹ́ wí pé wọ́n mọ ohun tí ń bẹ nínú kíkí ìrun alẹ́ – ‘Ishā’ – àti ìrun àárọ̀ (nínú oore) ni, dájúdájú wọn kò bá wá kí méjèèjì, kódà kó jẹ́ wí pé wọ́n yóò rákòrò wá síbẹ̀ niAl-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (615), Muslim sì gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (437).