languageIcon
search
search
beforeFajronColorIcon Àwọn Sunnah tí kò ní àsìkò/ Àwọn Sunnah ìrun pípè/ ( Iye òǹkà òpó-ìrun (rak‘ah) rẹ̀ 5 Àwọn Sunnah )
brightness_1 Wíwí ohun tí apèrun ń wí tẹ̀lé e

Sunnah ni fún ẹni tí ó bá gbọ́ ìpè-ìrun kí ó máa sọ irú ohun tí apèrun ń sọ, àyàfi nígbà tí apèrun bá wí pé: ayya ‘alaṣ-ṣalāh (ẹ yára wá kírun), tàbí ḥayya ‘alal-falāḥ (ẹ yára wá jèrè), yóò wí pé: “Lā ḥawla walā quwwata ’illā billāh (kò sí ọgbọ́n kankan, kò sì sí agbára kankan àyàfi pẹ̀lú Ọlọ́hun)”.

Nítorí Hadīth tí ‘Abdullāh ọmọ ‘Amr, ọmọ́ Al-‘Āṣ – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí àwọn méjèèjì – gbà wá pé:  Dájúdájú òun gbọ́ tí Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – ń sọ wí pé:  “Nígbà tí ẹ bá gbọ́ tí apèrun ń pèrun, ẹ máa sọ irú ohun tí ó ń sọ...” Muslim gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (384). Àti Hadīth tí ‘Umar ọmọ Al-Khaṭṭāb – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá, ó sọ wí pé:  Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – sọ wí pé: Nígbà tí apèrun bá sọ wí pé: Allāhu ’Akbar, Allāhu ’Akbar  (Ọlọ́hun ni Ó tóbi jùlọ, Ọlọ́hun ni Ó tóbi jùlọ), tí ẹni kẹ́ni nínú yín sì sọ wí pé: Allāhu ’Akbar, Allāhu ’Akbar  (Ọlọ́hun ni Ó tóbi jùlọ, Ọlọ́hun ni Ó tóbi jùlọ), lẹ́yìn náà tí ó bá sọ wí pé: ’Ashhadu ’an lā ’ilāha ’illallāh (Mo jẹ́rìí pé kò sí ọlọ́hun kan tí ó lẹ́tọ̀ọ́ sí ìjọsìn àyàfi Ọlọ́hun Allāh), tí òun náà sì sọ wí pé: ’Ashhadu ’an lā ’ilāha ’illallāh (Mo jẹ́rìí pé kò sí ọlọ́hun kan tí ó lẹ́tọ̀ọ́ sí ìjọsìn àyàfi Ọlọ́hun Allāh), lẹ́yìn náà tí ó bá sọ wí pé: ’Ashhadu ’anna Muḥammadan Rasūlullāh (Mo jẹ́rìí pé Ànábì  Muḥammad, níti pàápàá, jẹ́ Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun), tí òun náà sì sọ wí pé: ’Ashhadu ’anna Muḥammadan Rasūlullāh (Mo jẹ́rìí pé Ànábì Muḥammad, níti pàápàá, jẹ́ Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun), lẹ́yìn náà tí ó bá sọ wí pé: ayya ‘alaṣ-ṣalāh (Ẹ yára wá kírun), tí òun náà sì sọ wí pé: Lā ḥawla walā quwwata ’illā billāh (kò sí ọgbọ́n kankan, kò sì sí agbára kankan àyàfi pẹ̀lú Ọlọ́hun), lẹ́yìn náà tí ó bá sọ wí pé: Ḥayya ‘alal-falāḥ (ẹ yára wá jèrè), tí òun náà sì sọ wí pé: Lā ḥawla walā quwwata ’illā billāh (kò sí ọgbọ́n kankan, kò sì sí agbára kankan àyàfi pẹ̀lú Ọlọ́hun), lẹ́yìn náà tí ó bá sọ wí pé: Allāhu ’Akbar, Allāhu ’Akbar (Ọlọ́hun ni Ó tóbi jùlọ, Ọlọ́hun ni Ó tóbi jùlọ), tí òun náà sì sọ wí pé: Allāhu ’Akbar, Allāhu ’Akbar (Ọlọ́hun ni Ó tóbi jùlọ, Ọlọ́hun ni Ó tóbi jùlọ), lẹ́yìn náà tí ó bá sọ wí pé: Lā ’ilāha ’illallāh, (Mo jẹ́rìí pé kò sí ọlọ́hun kan tí ó lẹ́tọ̀ọ́ sí ìjọsìn àyàfi Ọlọ́hun Allāh), tí òun náà sì sọ wí pé: Lā ’ilāha ’illallāh, (Mo jẹ́rìí pé kò sí ọlọ́hun kan tí ó lẹ́tọ̀ọ́ sí ìjọsìn àyàfi Ọlọ́hun Allāh), tí ó jẹ́ wí pé ó ti ọkàn rẹ̀ wá, dájúdájú yóò wọ ọgbà-ìdẹ̀ra Al-Jannah” Muslim gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (385).

Nígbà tí apèrun bá ń pe àwọn èèyàn síbi ìrun àfẹ̀rẹ̀mọ́júmọ́ (pẹ̀lú gbólóhùn: Aṣ-ṣalātu khayrun min-nawm), dájúdájú òun náà yóò sọ irú ohun tí apèrun ń sọ: “Aṣ-ṣalātu khayrun min-nawm (ìrun kíkí lóore ju oorun lọ)”.

 

brightness_1 Ṣíṣe àsàlátù fún Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – lẹ́yìn ìrun pípè

Nítorí Ḥadīth tí ‘Abdullāh ọmọ ‘Amr – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí àwọn méjèèjì – gbà wá, ó sọ wí pé:  Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – sọ wí pé: “Nígbà tí ẹ bá gbọ́ apèrun tí ó ń pèrun, ẹ máa sọ irú ohun tí ó ń sọ, lẹ́yìn náà ẹ ṣe àsàlátù fún mi, nítorí pé dájúdájú ẹni kẹ́ni tí ó bá ṣe àsàlátù kan ṣoṣo fún mi, Ọlọ́hun yóò tóri rẹ̀ ṣe àsàlátù mẹ́wàá padà fún un. Lẹ́yìn náà ẹ tọrọ ipò Al-Wasīlah fún mi, nítorí pé ó jẹ́ ipò kan nínú ọgbà-ìdẹ̀ra Àlùjáńnà, kò sì lẹ́tọ̀ọ́ àyàfi fún ẹníkan ṣoṣo nínú àwọn ẹrúsìn Ọlọ́hun, mo sì ǹ rankàn kí ó jẹ́ wí pé èmi ni ẹni náà. Nítorí náà ẹni kẹ́ni tí ó bá  tọrọ ipò Al-Wasīlah fún mi, ìṣìpẹ̀ mi ti di ẹ̀tọ́ fún un” Muslim gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (384).

Èyí tí ó lọ́lá jùlọ nínú àwọn ìran àsàlátù ni Aṣ-ṣalātul-Ibrāhīmiyyah:Allāhumma ṣalli ‘alā Muḥammad, wa‘alā ’āli Muḥammad, kamā ṣallayta ‘alā Ibrāhīm... (Ìrẹ Ọlọ́hun! Ṣe ìkẹ̀ fún Ànábì Muḥammad àti fún àwọn ará ilé Ànábì Muḥammad, gẹ́gẹ́ bí O ti ṣe ìkẹ̀ fún Ànábì Ibrāhīm..)”.