languageIcon
search
search
beforeFajronColorIcon Àwọn Sunnah tí kò ní àsìkò/ Àdúà Ṣíṣe / ( Iye òǹkà òpó-ìrun (rak‘ah) rẹ̀ 9 Àwọn Sunnah )
brightness_1 Kí ó máa ṣe àdúà nígbà tí ó bá wà lórí ìmọ́ra

Nítorí Ḥadīth tí Abū Mūsā – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá, tó wá nínú Ṣaḥīḥu méjèèjì àti ìtàn rẹ̀ pẹ̀lú arákùnrin bàbá rẹ̀, tí ń jẹ́ Abū ‘Āmir – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i –, nígbà tí Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – fi ṣe ọ̀gá lórí àwọn ọmọ-ogun tó rán lọ sí ’Awṭās, ó wà nínú Ḥadīth náà pé: Wọ́n pa Abū ‘Āmir – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i –, ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún Abū Mūsā – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i –  pé kí ó bá òun sálámà sí Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a –, kí ó sì sọ fún un pé kí ó ṣe àdúà fún òun. Abū Mūsā sọ wí pé: “Nítorí náà mo fún un ní ìró nípa ohun tó ṣẹlẹ̀ sí wa àti ohun tó ṣẹlẹ̀ sí Abū ‘Āmir. Mo sì sọ fún un pé: Ó sọ (fún mi) pé: Sọ fún un pé kí ó tọrọ àforíjìn fún mi. Ni Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – bá béèrè fún omi, ó sì ṣe àlùwàlá nínú rẹ̀, lẹ́yìn náà ó gbé ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì sókè, lẹ́yìn náà ó sọ wí pé: “Allāhummaghfir li‘Ubayd, ’Abī ‘Āmir (Ìrẹ Ọlọ́hun! Ṣe àforíjìn fún ‘Ubayd, bàbá ‘Āmir)”. Títí tí mo fi rí fífunfun abíyá rẹ̀ méjèèjì. Lẹ́yìn náà ó sọ wí pé: “Allāhummaj‘alhu yawmal-Qiyāmati fawqa kathīrin min khalqik, ’aw minan-nās (Ìrẹ Ọlọ́hun! Jẹ́ kí ó wà, ní ọjọ́ Ìgbéǹde, ní òkè ọ̀pọ̀lọpọ̀ nínú àwọn ẹ̀dá Rẹ, tàbí nínú àwọn èèyàn)”. Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (4323), Muslim gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (2498).

brightness_1 Dída ojú kọ Gábàsì

‘Abdullāh ọmọ ‘Amr – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí àwọn méjèèjì – sọ wí pé: ‘Umar ọmọ Al-Khaṭṭāb – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – bá mi sọ̀rọ̀, ó sọ wí pé: Nígbà tí ó di ọjọ́ ogun Badr, Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – ṣíjú wo àwọn ọ̀ṣẹbọ, wọ́n sì jẹ́ ẹgbẹ̀rún kan, àwọn sàábé rẹ̀ sì jẹ́ ọgọ́rùn-ún mẹ́ta lé ní mọ́kàndínlógún ọkùnrin, Ọjíṣẹ́ Ọlọ́hun dojú kọ Gábàsì, lẹ́yìn náà ó tẹ́ ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì pẹrẹsẹ, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní pe Ọlọ́hun Ọba rẹ̀: “Ìrẹ Ọlọ́hun! Pé àdéhùn tí Ó bá mi ṣe fún mi. Ìrẹ Ọlọ́hun! Fún mi ní ohun tí  Ó ṣe àdéhùn rẹ̀ fún mi. Ìrẹ Ọlọ́hun! Tí àkójọpọ̀ àwọn Mùsùlùmí yìí bá parun, wọn kò ní sìn Ẹ́ mọ́ lórí ilẹ̀”. Kò yé máa pe Ọlọ́hun Ọba rẹ̀, ní ẹni tó tẹ́ ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì pẹrẹsẹ, tí ó sì dojú kọ Gábàsì, títí tí èwù rẹ̀ fi yẹ̀ kúrò níbi èjìká rẹ̀ méjèèjì. Ni Abū Bakr bá wá bá a, ó sì mú èwù rẹ̀, o fi bo èjìká rẹ̀ méjèèjì padà, lẹ́yìn náà ó dì mọ́ ọn láti ẹ̀yìn, ó sì sọ wí pé: Ìrẹ Ọjíṣẹ́ Ọlọ́hun, pípè tí ó ń pe Ọlọ́hun Ọba rẹ tí tó ọ, nítorí pé dájúdájú yóò mú àdéhùn tí Ó ṣe fún ọ ṣẹ...”.  Muslim gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (1763).

brightness_1 Pípe Ọlọ́hun – Ọba tí Ọlá Rẹ̀ ga – pẹ̀lú àwọn Ọrúkọ Rẹ̀ tó dára jùlọ

Nítorí náà yóò ṣẹ̀ṣà nínú àwọn Ọrúkọ Ọlọ́hun tó dára jùlọ, èyí tó bá ohun tí ó ń tọrọ mu, tí ó sì ṣe déédé pẹ̀lú rẹ̀. Tí ó bá ń tọrọ arísìkí lọ́dọ̀ Ọlọ́hun – mímọ́ ni fún Un –, yóò sọ wí pé: “Yā Razzāq (Ìrẹ Ọlọ́hun, Ọba Ọlọ́pọ̀lọpọ̀ arísìkí”. Tí ó bá ń tọrọ ìkẹ́ lọ́dọ̀ Ọlọ́hun – Ọba tí Ọlá Rẹ̀ ga –, yóò sọ wí pé: “Yā Raḥmān, yā Raḥīm (Ìrẹ Ọlọ́hun, Ọba Àjọkẹ́ ayé, Ọba Àṣàkẹ́ Ọ̀run”. Tí ó bá ń tọrọ iyì lọ́dọ̀ Ọlọ́hun – Ọba Abiyì, tí Ó gbọn-n-gbọ́n –,  yóò sọ wí pé: “Yā ‘Azīz (Ìrẹ Ọlọ́hun, Ọba Abiyì). Tí ó bá ń tọrọ àforíjìn lọ́dọ̀ Ọlọ́hun – Ọba Abiyì, tí Ó gbọn-n-gbọ́n –, yóò sọ wí pé: “Yā Ghafūr (Ìrẹ Ọlọ́hun, Ọba Ọlọ́pọ̀lọpọ̀ àforíjìn”. Tí ó bá ń tọrọ ìwòsàn lọ́dọ̀ Ọlọ́hun Rẹ̀, yóò sọ wí pé: “Yā Shāfī (Ìrẹ Ọlọ́hun, Ọba tí Ó máa ń woni sàn”.

Báyìí ni yóò ṣe máa pe Ọlọ́hun pẹ̀lú ohun tó bá àdúà rẹ̀ mu, nítorí Ọ̀rọ̀ Ọlọ́hun – Ọba tí Ọlá Rẹ̀ ga – tí Ó sọ wí pé: “Àti pé ti Ọlọ́hun ni àwọn orúkọ tó dára jùlọ, nítorí náà ẹ pè É pẹ̀lú wọn” (Al-’A‘rāf: 180).

brightness_1 La ripetizione e l’insistenza nell’invocazione

Nel succitato detto profetico tramandato da ibn ‘Abbas (Allah sia soddisfatto d’entrambi) il Profeta (Allah lo benedica e gli dia la pace) ebbe a dire: “O Allah, realizza per me quel che mi hai promesso; o Allah, concedimi quel che mi hai promesso”. Continuò ad invocare l’Altissimo, fino a che cadde il mantello dalle sue spalle. Abu Bakr lo raccolse e lo ripose sulle sue spalle, dicendo: “O Profeta di Allah, la tua invocazione è sufficiente …” (Muslim, 1763).

Pure ciò è confermato dalla tradizione profetica tramandata da Abu Hurayrah (Allah sia soddisfatto di lui), allorché il Profeta (Allah lo benedica e gli dia la pace) elevò un’invocazione a favore del clan dei Daws: “O Allah guida i Daws e conducili a noi, O Allah guida i Daws e conducili a noi” (Bukhari, 2937; Muslim, 2524).

Un’altra evidenza è costituita dal detto profetico: “… uno affronta un lungo viaggio, che lo affatica e lo segna, poi leva le mani al cielo [ed esclama]: o Signore, o Signore…” (Muslim, 1015). La ripetizione qui sta ad indicare l’insistenza [necessaria nell’invocazione ad Allah].

Fa parte della Sunnah ripetere l’invocazione tre volte, come riportato da Ibn Mas’ud (Allah sia soddisfatto di lui) che disse che quando [il Profeta] invocava [Allah] o Gli rivolgeva una richiesta, lo faceva per tre volte. E disse tre volte: “O Allah, tratta i Quraysh come meritano!” (Bukhari, 240; Muslim, 1794).

brightness_1 Kín ni màá sọ níbi àdúà mi?

Àǹfààní kan: Ẹlòmíràn le béèrè pé: Kín ni màá sọ níbi àdúà mi?

Èsì rẹ̀ ni pé: Tọrọ ohun tí ó bá fẹ́ nínú àwọn nǹkan ayé àti Ọ̀run, sì ṣe ojú kòkòrò láti máa lo àwọn gbólóhùn kékeré, tó kó ìtumọ̀ tó pọ̀ sínú, níbi àdúà rẹ. Èyí ni àwọn àdúà tó wá nínú Tírà Ọlọ́hun àti Sunnah Ànábì. Ìbéèrè nípa oore ayé àti ti Ọ̀run wà níbẹ̀. Tún ronú sí ìbéèrè tí ń bọ̀ yìí, nígbà tí wọ́n ṣẹ́rí rẹ̀ sí Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a –, tí ó sì dáhùn pẹ̀lú àwọn gbólóhùn tó tóbi, èyí tí ó kó oore ayé àti Ọ̀run sínú fún Mùsùlùmí. Irú ìró ìdùnnú wo ni ó tún wá tó èyí, ẹ̀bún wo ni ó tún tóbi jù ú lọ! Nítorí náà dírọ̀ mọ́ wọn, kí ó sì ronú sí wọn.

Abū Mālik Al-’Ashja‘ī gbà á wá láti ọ̀dọ̀ bàbá rẹ̀  – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí àwọn méjèèjì – pé: Dájúdájú òun gbọ́ Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a –, nígbà tí ọkùnrin kan wá bá a, tí ó sí sọ pé: Ìrẹ Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun! Báwo ni máa ti máa sọ, nígbà tí mo bá ń tọrọ nǹkan lọ́wọ́ Ọlọ́hun Ọba mi? Ó dáhùn pé: “Máa sọ wí pé: “Allāhummaghfir lī, warḥamnī, wa‘āfinī, warzuqnī (Ìrẹ Ọlọ́hun! Forí jìn mí, kẹ́ mi, wò mí sàn, sì pèsè fún mi)”. Yóò kò àwọn ọmọ ìka ọwọ́ rẹ̀ jọ àyàfi àtàǹpàkò, “dájúdájú èyí yóò kó oore ayé rẹ àti Ọ̀run rẹ jọ papọ̀ fún ọ”. Muslim gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (2697).

Nínú ẹ̀gbàwá mìíràn tó gbà wá: Tí ẹnì kan bá gba ẹ̀sìn Islām, Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – yóò kọ́ ọ ní ìrun kíkí, lẹ́yìn náà yóò pa á láṣẹ pé kí ó máa bẹ Ọlọ́hun pẹ̀lú àwọn gbólóhùn yìí: “Allāhummaghfir lī, warḥamnī, wahdinī,  wa‘āfinī, warzuqnī (Ìrẹ Ọlọ́hun! Forí jìn mí, kẹ́ mi, fi mí mọ̀nà, wò mí sàn, sì pèsè fún mi)”. Muslim gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (2697).