languageIcon
search
search
beforeFajronColorIcon Àwọn Sunnah tó ní àsìkò/ Àsìkò tó síwájú yíyọ àfẹ̀rẹ̀mọ́júmọ́ ( Iye òǹkà òpó-ìrun (rak‘ah) rẹ̀ 2 Àwọn àkòrí ọ̀rọ̀ )
brightness_1 Nínú ohun tí ó bá Sunnah mu ni kí ó kírun òru ní àsìkò rẹ̀ tí ó lọ́lá jùlọ

Tí wọ́n bá bi wá pé: Àsìkò wo ni ó lọ́lá jùlọ fún ìrun òru?

Ìdáhùn nìyí: Nínú ohun tí a ti mọ̀ ni wí pé, dájúdájú àsìkò ìrun Witr máa ń bẹ̀rẹ̀ láti ẹ̀yìn ìrun alẹ́ títí ìgbà tí àfẹ̀rẹ̀mọ́júmọ́ yóò fi yọ. Nítorí náà àsìkò ìrun Witr  wà láàrin ìrun alẹ́ àti yíyọ àfẹ̀rẹ̀mọ́júmọ́.

Ẹ̀rí rẹ̀ ni :

Ḥadīth tí ‘Ā’ishah – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá, ó sọ wí pé:  “Ànábì  – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a –máa ń kí, láàrin ìgbà tí ó bá ti kírun alẹ́ tán sí ìgbà tí  àfẹ̀rẹ̀mọ́júmọ́ yóò fi yọ; òpó ìrun mọ́kànlá, ó máa ń sálámà láàrin gbogbo òpó ìrun méjì, yóò sì fi ẹyọ̀nka ṣe ìrun Witr” Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (2031), Muslim sì gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (736).

Nípa àsìkò tó lọ́lá jùlọ fún ìrun òru, èyí ni: Ìdámẹ́ta òru, lẹ́yìn ìlàjì rẹ̀.

Ohun tí a gbà lérò ni: Kí ènìyàn pín òru sí ìlàjì, ìlàjì, kí ó sì dìde kírun òru níbi ìdámẹ́ta nínú ìlàjì òru kejì, kí ó sì sùn ní ìgbẹ̀yìn òru. Ìtumọ̀ èyí ni pé: Yóò dìde kírun òru níbi ìdámẹ́fà kẹrin àti ìkarùn-ún, yóò sì sùn níbi ìdámẹ́fà ẹlẹ́ẹ̀kẹfà.

Ẹ̀rí rẹ̀ ni : Ḥadīth tí ‘Abdullāh ọmọ ‘Amr – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí àwọn méjèèjì – gbà wá, ó sọ wí pé: Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – sọ wí pé: “Dájúdájú ààwẹ̀ tí Ọlọ́hun fẹ́ràn jùlọ ni ààwẹ̀ Ànábì Dāwūd, ìrun tí Ọlọ́hun sì fẹ́ràn jùlọ ni ìrun Ànábì Dāwūd – kí ọlà Ọlọ́hun máa bá a –, ó máa ń fi ìlàjì òru sùn, yóò sì fi ìdámẹ́ta rẹ̀ dìde kírun, yóò tún fi ìdámẹ́fà rẹ̀ sùn, ó sì máa ń fi ọjọ́ kan gba ààwẹ̀, yóò fi ọjọ́ kejì ṣínu”  Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (3420), Muslim sì gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (1159).

– Tí ènìyàn bá fẹ́ lo Sunnah yìí, báwo ni yóò ti ṣe ìṣirò òru rẹ̀?

Yóò ṣírò àsìkò rẹ̀ láti ìgbà tí òòrùn bá ti wọ̀ títí tí  àfẹ̀rẹ̀mọ́júmọ́ yóò fi yọ. Lẹ́yìn náà yóò pín in sí ọ̀nà mẹ́fà, ìpín mẹ́ta àkọ́kọ́, èyí ni ìdáméjì àkọ́kọ́ nínú òru, yóò dìde kírun lẹ́yìn rẹ̀, èyí túmọ̀ sí wí pé: Yóò dìde kírun níbi ìdámẹ́fà kẹrin àti ìkarùn-ún. Nítorí pé dájúdájú èyí ni a ó kà sí ìdámẹ́ta òru. Lẹ́yín náà yóò sùn níbi ìdámẹ́fà ìgbẹ̀yìn, èyí ni ìdámẹ́fà kẹfà. Ìdí nìyí, tí ‘Ā’ishah – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – fi sọ wí pé: “Àsìkò sààrì kò bá a (Ànábì)  – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – ní ọ̀dọ̀ mi rí, àyàfi kí ó máa sùn lọ́wọ́”  Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (3420), Muslim sì gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (1159).

Èyí ni ọ̀nà tí Mùsùlùmí yóò tọ̀ tí yóò fi wà ní àsìkò tí ó lọ́lá jùlọ fún kíkírun ní òru, gẹ́gẹ́ bí ó ti wá nínú Ḥadīth tí ‘Abdullāh ọmọ ‘Amr – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí àwọn méjèèjì – gbà wá, èyí tí ó ti síwájú.

Kókó ọ̀rọ̀ yìí, ní ṣókí, ni pé: Jíjẹ́ èyí tí ó lọ́lá jùlọ àsìkò dídìde kírun lóru wà lórí ìpele mẹ́ta:

Ìpele Àkọ́kọ́:  Kí èèyàn fi ìlàjì òru àkọ́kọ́ sùn, lẹ́yìn náà yóò fi ìdámẹ́ta rẹ̀ dìde kírun, lẹ́yìn náà yóò fi ìdámẹ́fà rẹ̀ sùn – gẹ́gẹ́ bíi àlàyé tí ó ti siwájú –.

Ẹ̀rí rẹ̀ ni : Ḥadīth tí ‘Abdullāh ọmọ ‘Amr, ọmọ ‘Āṣ – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí àwọn méjèèjì – gbà wá, èyí tí ó ti síwájú láìpẹ́.

Ìpele Kejì: Kí èèyàn dìde kírun níbi ìdámẹ́ta tí ó gbẹ̀yìn nínú òru.

Ẹ̀rí rẹ̀ ni :

Ḥadīth tí Abū Hurayrah – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá pé; dájúdájú Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – sọ wí pé: “Ọlọ́hun Ọba wa, Oníbùkún, Ọba tí ọlá Rẹ̀ ga, máa ń sọ̀kalẹ̀, ní gbogbo òru, sí sánmà ilé-ayé, nígbà tí ó bá ṣẹ́kù ìdámẹ́ta tí ó gbẹ̀yìn nínú òru, yóò máa sọ wí pé: Tani yóò pè Mí, máa sì dá a lóhùn, tani yóò tọrọ nǹkan lọ́dọ̀ Mi, máa sì fún un, tani yóò tọrọ àforíjìn lọ́dọ̀ Mi, máa sì ṣe àforíjìn fún un” Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (1145), Muslim sì gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (758). Bẹ́ẹ̀ náà ni Ḥadīth tí Jābir – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá, ó ń bọ̀ lọ́nà.

Tí ó bá ń bẹ̀rù pé òun le má jí dìde ní ìgbẹ̀yìn òru, kí ó rí i pé òun kírun ní ìbẹ̀rẹ̀ rẹ̀, tàbí ní ìgbàkíìgbà tí ó bá rọ̀ ọ́ lọ́rùn ní òru, èyí ni ìpele kẹta.

Ìpele Kẹta: Kí ó kírun ní ìbẹ̀rẹ̀ òru, tàbí ní ìgbàkíìgbà tí ó bá rọ̀ ọ́ lọ́rùn ní òru.

Ẹ̀rí rẹ̀ ni :

Ḥadīth tí Jābir – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá, ó sọ wí pé: Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – sọ wí pé: Ẹni kẹ́ni  tí ó bá ń bẹ̀rù pé òun kò ní jí dìde kírun ní ìgbẹ̀yìn òru, kí ó rí i pé òun kírun Witr ní ìbẹ̀rẹ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹní tí ó bá ń rankàn pé òun yóò jí dìde kírun ní ìgbẹ̀yìn rẹ̀, kí ó kírun Witr ní ìgbẹ̀yìn òru, nítorí pé dájúdájú ìrun ìgbẹ̀yìn òru jẹ́ ohun tí àwọn Malā’kah máa ń kópa níbẹ̀, èyí ni ó sì lọ́lá jùlọ” Muslim gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (755).

Bákan náà, a ó gbé àsọtẹ́lẹ̀ Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a –, fún Abū Dharr, lórí rẹ̀. (An-Nasā’ī gbà á wá nínú As-sunanul-Kubrā {2712}), Al-Albānī kà á sí ẹ̀gbàwá tí ó ní àlááfíà nínú (Aṣ-Ṣaḥīḥah, 2166). Àti fún Abū Ad-Dardā’ (Aḥmad gbà á wá pẹ̀lú òǹkà {27481}), àti (Abū Dāwūd pẹ̀lú òǹkà {1433}), Al-Albānī kà á sí ẹ̀gbàwá tí ó ní àlááfíà nínú (Ṣaḥīḥu Abī Dāwūd, 5/177). Àti fún Abū Hurayrah – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i –, Muslim gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (737). Kálukú wọn sọ wí pé: “Ààyò mi sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún pẹ̀lú nǹkan mẹ́ta”, ó sì dárúkọ nínú rẹ̀: “Àti pé kí n máa kírun Witr síwájú kí n tó sùn”.

brightness_1 Nínú Sunnah ni kí ó ṣe àwọn àdúà ìbẹ̀rẹ̀-ìrun, èyí tí ó wà nípa ìrun òrun

Nínú Sunnah ni kí ó ṣe àwọn àdúà ìbẹ̀rẹ̀-ìrun, èyí tí ó wà nípa ìrun òrun. Nínú rẹ̀ ni:

a. Ohun tí ó wá nínú Ṣaḥīḥu Muslim, nínú  Ḥadīth tí ‘Ā’ishah – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá, ó sọ wí pé: “Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – nígbà tí ó bá dìde lóru láti kírun máa ń bẹ̀rẹ̀ ìrun rẹ̀ pẹ̀lú: Allāhumma Rabba Jabrā’īl, waMīkā’īl, wa’Isrāfīl, Fāṭiras-samāwāti wal-’arḍ, ‘Ālimal-ghaybi wash-shahādah, ’Anta taḥkumu bayna ‘ibādika fīmā kānū fīhi yakhtalifūn. Ihdinī limakh-tulifa fīhi minal-ḥaqqi bi-’idhnik, ’innaka tahdī man tashā’u ’ilā ṣirātin mustaqīm (Ìrẹ Ọlọ́hun, Ọlọ́hun Ọba Jabrā’īl, Mīkā’īl àti Isrāfīl. Olùṣẹ̀dá àwọn sánmà àti ilẹ̀. Olùmọ ìkọ̀kọ̀ àti gbangba.  Ìwọ ni Ó ṣe ìdájọ́ láàrin àwọn ẹrúsin Rẹ níbi ohun tí wọ́n ń ṣe ìyapa ẹnu nípa rẹ. Fi mí mọ̀nà lọ síbi òdodo tí wọ́n ń yapa ẹnu nípa rẹ pẹ̀lú ìyọ̀ǹda Rẹ. Dájúdájú Ìwọ ni O máa ń fi ẹni tí O fẹ́ mọ̀nà lọ síbi ọ̀nà tí ó dúró tọ́)” Muslim gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (770).

b. Ohun tí ó wá nínú nínú Ṣaḥīḥu méjèèjì nínú Ḥadīth Ibn ‘Abbās – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí àwọn méjèèjì – gbà wá, ó sọ wí pé: “Ànábì Ọlọ́hun  – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – nígbà tí ó bá fẹ́ kírun lóru máa ń sọ wí pé: “Allāhumma lakal-ḥamd, ’Anta Nūrus-samāwāti wal-’arḍi, walakal-ḥamd, ‘Anta Qayyimus-samāwāti wal-’arḍi, walakal-ḥamd, ’Anta Rabbus-samāwāti wal-‘arḍi waman fīhinn, ’Antal-Ḥaqq, wawa‘dukal-ḥaqq, waqawlukal-ḥaqq, waliqā’ukal-ḥaqq, wal-jannatu ḥaqqun wan-nāru ḥaqq, wan-Nabiyyūna ḥaqq, was-sā‘tu ḥaqq. Allāhumma laka ’aslamtu, wabika ’āmant, wa‘alayka tawakkalt, wa-’ilayka ’anabt, wabika khāṣamt, wa’ilayka ḥākamt, faghfir lī mā qaddamt, wamā ’akhkhart, wamā ’asrart, wamā ’a‘lant, ’Anta ’ilāhī lā ’ilāha ’illā ’Ant (Ìrẹ Ọlọ́hun! Gbogbo ọpẹ́ àti ẹyìn tì Ẹ ni í ṣe, Ìwọ ni ìmọ̀lẹ̀ àwọn sánmà àti ilẹ̀. Gbogbo ọpẹ́ àti ẹyìn tì Ẹ ni í ṣe, Ìwọ ni Alákòóso àwọn sánmà àti ilẹ̀. Gbogbo ọpẹ́ àti ẹyìn tì Ẹ ni í ṣe, Ìwọ ni Ọlọ́hun Ọba àwọn sánmà àti ilẹ̀ àti gbogbo ohun tí ń bẹ nínú àwọn méjèèjì. Ìwọ ni Òdodo, àdéhùn Rẹ òdodo ni, Ọ̀rọ̀ Rẹ òdodo ni, òdodo ni pípàdé Rẹ, Ọgbà-ìdẹ̀ra Àlùjánńà òdodo ni, òdodo ni Iná, òdodo ni àwọn Òjíṣẹ́ Ọlọ́hun, òdodo sì ni àkókò Ìgbéǹde. Ìrẹ Ọlọ́hun! Ìwọ ni mo gbàfà fún; Ìwọ ni mo gbàgbọ́, Ìwọ ni mo gbára lé, ọ̀dọ̀ Rẹ ni mò ń ṣẹ́rí padà sí, Ìwọ ni mo ń jà fún, ọ̀dọ̀ Rẹ sì ni mò ń wá ìdájọ́ sí. Nítorí náà forí ẹ̀ṣẹ̀ tí mo tì síwájú, àti èyí tí mo fi kẹ́yìn, àti èyí tí mo dá ní ìkọ̀kọ̀ àti èyí tí mo dá ní gbangba jìn mí. Ìwọ ni Ọlọ́hun mi, kò sí ọlọ́hun kankan tó lẹ́tọ̀ọ́ sí ìjọsìn àyàfi Ìwọ níkan)Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (7499), Muslim sì gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (768).

brightness_1 Kí ó ṣe àwọn Sunnah tí ó wá nípa kíkéwú rẹ̀ (lórí ìrun)

Kí ó ṣe àwọn Sunnah tí ó wá nípa kíkéwú rẹ̀ (lórí ìrun), nínú rẹ̀ ni:

a. Kí ó ké Al-Qur’ān (lórí ìrun) pẹ̀lú pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́. Ohun tí a gbà lérò ni pé: Kó ní yára tàbí kí ó máa sáré ké Al-Qur’ān.

b. Kí ó máa dákẹ́ lórí ’āyah kọ̀ọ̀kan tí ó bá ń ké nínú Al-Qur’ān. Ohun tí a gbà lérò ni pé: Kó gbọdọ̀ máa jan ’āyah méjì tàbí mẹ́ta papọ̀ láìdúró, ṣùgbọ́n yóò máa dúró lórí gbogbo ’āyah kọ̀ọ̀kan.

d. Nígbà tí ó bá rékọjá níbi ’āyah tí ń sọ̀rọ̀ nípa ṣíṣe àfọ̀mọ́ fún Ọlọ́hun, yóò ṣe àfọ̀mọ́ fún Un, nígbà tí ó bá rékọjá níbi ’āyah tí ń sọ̀rọ̀ nípa títọrọ nǹkan lọ́dọ̀ Ọlọ́hun, yóò tọrọ lọ́dọ̀ Rẹ, nígbà tí ó bá rékọjá níbi ’āyah tí ń sọ̀rọ̀ nípa wíwá ìṣọ́ pẹ̀lú Ọlọ́hun, yóò wá ìṣọ́ pẹ̀lú Rẹ̀.

Ìtọ́ka àwọn ohun tí ó síwájú yìí ni:

Ḥadīth tí Ḥudhayfah – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá, ó sọ wí pé: “Mo kírun pẹ̀lú Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – ní òru ọjọ́ kan, ó sì bẹ̀rẹ̀ Sūratul-Baqarah, ní mo bá sọ (sí ẹ̀mí mi) pé: Yóò rùkúù nígbà tí ó bá dé ’āyah ọgọ́rùn-ún, lẹ́yìn náà ó tẹ̀ síwájú, ní mo bá sọ (sí ẹ̀mí mi) pé: Yóò kí òpó-ìrun kan pẹ̀lú rẹ̀, ṣùgbọ́n ó tẹ̀ síwájú, ní mo bá sọ (sí ẹ̀mí mi) pé: Yóò rùkúù pẹ̀lú rẹ̀, lẹ́yìn náà ó bẹ̀rẹ̀ Sūratun-Nisā’, ó sì kà á parí, lẹ́yìn náà ó bẹ̀rẹ̀ Sūratu ’Āl-‘Imrān, ó sì kà á parí. Ó ń kéwú pẹ̀lú pẹ̀lẹ́pẹ̀lẹ́, nígbà tí ó bá rékọjá pẹ̀lú ’āyah tí ń sọ̀rọ̀ nípa ṣíṣe àfọ̀mọ́ fún Ọlọ́hun, yóò ṣe àfọ̀mọ́ fún Un, nígbà tí ó bá rékọjá pẹ̀lú ’āyah tí ń sọ̀rọ̀ nípa títọrọ nǹkan lọ́dọ̀ Ọlọ́hun, yóò tọrọ lọ́dọ̀ Rẹ, nígbà tí ó bá rékọjá pẹ̀lú ’āyah tí ń sọ̀rọ̀ nípa wíwá ìṣọ́ pẹ̀lú Ọlọ́hun, yóò wá ìṣọ́ pẹ̀lú Rẹ̀, lẹ́yìn náà ó rùkúù, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí sọ wí pé: Subḥāna Rabbiyal-‘Aẓīm (Mímọ́ ni fún Ọlọ́hun Ọba mi, Ọba tí Ó tóbi)”. Àsìkò tí ó lò ní rùkúù sì súnmọ́ èyí tí ó lò ní ìnàró. Lẹ́yìn náà ó sọ wí pé: Sami‘allāhu liman ḥamidah (Ọlọ́hun gbọ́ ẹyìn ẹni tí ó yìn Ín)”. Lẹ́yìn náà ó náró fún ìgbà tí ó pẹ́, tí ó súnmọ́ àsìkò tí ó fi rùkúù. Lẹ́yìn náà ó foríkanlẹ̀, ó sì wí pé: Subḥāna Rabbiyal-’A‘lā (Mímọ́ ni fún Ọlọ́hun Ọba mi, Ọba tí Ó ga jùlọ)”, àsìkò tí ó lò níbi ìforíkanlẹ̀ rẹ̀ sì súnmọ́ èyí tí ó lò ní ìnàró” Muslim gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (772).

Àti nítorí ohun tí Aḥmad – kí Ọlọ́hun kẹ́ ẹ – gbà wá nínú tírà rẹ̀; Musnad, nínú Ḥadīth Umm salamah –kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá pé: Dájúdájú wọ́n bi í léèrè nípa bí Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – ṣe máa ń ké Al-Qur’ān, ó sì dádùn pé: Ó máa ń gé ohun tí ó bá ké nínú Al-Qur’ān ’āyah, ’āyah: }Bismillāḥir-Raḥmānir-Raḥīm $ Al-ḥamdu lillāhi Rabbil-‘ālamīn $ Ar-Raḥmānir-Raḥīm $ Māliki yawmid-Dīn ((Mo bẹ̀rẹ̀) pẹ̀lú Orúkọ Ọlọ́hun Allāh, Ọba Àjọkẹ́ Ayé, Ọba Àṣàkẹ́ Ọ̀run $ Gbogbo ọpẹ́ àti ẹyìn ti Ọlọ́hun ni í ṣe, Ọba Olùtọ́jú gbogbo àgbáyé $ Ọba Àjọkẹ́ Ayé, Ọba Àṣàkẹ́ Ọ̀run $ Olùkápá Ọjọ́ ẹ̀san)} Aḥmad gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (26583), Ad-Dāruquṭnī (118) sọ wí pé: “Ojúpọ̀nà rẹ̀ ní àlááfìà, ẹni tí ọkàn balẹ̀ sí ni gbogbo àwọn tí ó gbà á wá”, An-Nawawī kà á sí ẹ̀gbàwá tí ó ní àlááfìà nínú (Al-Majmū‘ 3/333).

 

brightness_1 Nínú Sunnah ni kí ó ṣe àdúà qunūt, níbi ìrun Witr, ní ẹ̀ẹ̀kọ̀ọ̀kan

Ohun tí a gbà lérò níbi yìí ni: Ṣíṣe àdúà, èyí yóò wáyé níbi òpó-ìrun kẹta, èyí tí yóò ka Sūratul-’Ikhlāṣ níbẹ̀.

Ṣíṣe àdúà qunūt níbi ìrun Witr, nínú Sunnah ni ṣíṣe é ní ẹ̀ẹ̀kọ̀ọ̀kan, nítorí pé ó fi ẹ̀sẹ̀ rinlẹ̀ láti ọ̀dọ̀ apákan nínú àwọn sàábé – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí wọn –, àti fífi í sílẹ̀ ní ẹ̀ẹ̀kọ̀ọ̀kan. Èyí ni Shaykhul-Islām, Ibn Taymiyyah – kí Ọlọ́hun kẹ́ ẹ – ṣà lẹ́ṣà. Ohun tí ó sì dára jùlọ ni kí pípa á tì pọ̀ ju ṣíṣe é lọ.

Ìbéèrè: Ṣé akírun yóò tẹ́ ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì níbi àdúà qunūt bí?

Ohun tí ó ní àlááfíà ní pé: Dájúdájú yóò tẹ́ ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì, èyí ni ohun tí ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ àwọn onímímọ̀ – kí  Ọlọ́hun kẹ́ wọn – sọ, nítorí pé èyí fi ẹ̀sẹ̀ rinlẹ̀ láti ọ̀dọ̀ ‘Umar – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gẹ́gẹ́ bí ó ti wà lọ́dọ̀ Al-Bayhaqī, ó sì kà á sí ẹ̀gbàwá tí ó ní àlááfìà.

Al-Bayhaqī – kí Ọlọ́hun kẹ́ ẹ – sọ wí pé: “Àwọn kan nínú àwọn sàábé – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí wọn – gbé ọwọ́ wọn sókè níbi àdúà qunūt”. Wo: As-Sunanul-Kubrā (2/211). 

Ìbéèrè: Kín ni yóò fi bẹ̀rẹ̀ àdúà qunūt rẹ̀ níbi ìrun Witr?

Ọ̀rọ̀ tí ó tẹ̀wọ̀n – Ọlọ́hun ni Ó mọ̀ jùlọ – ni pé dájúdájú yóò bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú dídúpẹ́ fún Ọlọ́hun, Ọba tí Ọlá Rẹ̀ ga, àti ṣíṣe ẹyìn fún Un, lẹ́yìn náà yóò ṣe àsàlátú fún Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a –, lẹ́yìn náà yóò ṣe àdúà, nítorí pé èyí ni ó súnmọ́ jùlọ fún gbígba àdúà.

Ẹ̀rí rẹ̀ ni :

Ḥadīth tí Faḍālah ọmọ ‘Ubayd – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá, ó sọ wí pé: “Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – gbọ́ tí ọkùnrin kan ń ṣe àdúà lórí ìrun rẹ̀, ṣùgbọ́n kò ṣe àsàlátú fún Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a –, nítorí náà Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – sọ wí pé: “Ẹni yìí kánjú, lẹ́yìn náà ó pè é, ó sì sọ fún un àti ẹlòmíràn yàtọ̀ sí i pé: “Tí ẹni kẹ́ni nínú yín bá ń kírun, kí ó bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú dídúpẹ́ fún Ọlọ́hun àti ṣíṣe ẹyìn fún Un, lẹ́yìn náà kí ó ṣe àsàlátú fún Ànábì, lẹ́yìn náà kí ó tọrọ ohun tí ó bá fẹ́ ní ọ̀dọ̀ Ọlọ́hun”  At-Tirmidhī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (3477), ó sì sọ wí pé: “Èyí jẹ́ Ḥadīth tí ó dára, tí ó sì ní àlááfìà”.

Ibn Al-Qayyim – kí Ọlọ́hun kẹ́ ẹ – sọ wí pé: “Ohun  tí a fẹ́, nínú ẹ̀sìn Islām, níbi àdúà ni kí ẹni tí ń ṣe àdúà bẹ̀rẹ̀ pẹ̀lú dídúpẹ́ fún Ọlọ́hun àti ṣíṣe ẹyìn fún Un síwájú kí ó tó sọ bùkáátà rẹ̀, lẹ́yìn náà yóò béèrè ohun tí ó bùkáátà sí, gẹ́gẹ́ bí ó ti wà nínú Ḥadīth tí Faḍālah ọmọ ‘Ubayd – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá”. Wo: Al-Wābiluṣ-Ṣayyib (ojú-ewé: 110).

Ìbéèrè :  Ṣé yóò fi ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì pá ojú rẹ̀ lẹ́yìn àdúà qunūt bí?

Ohun tí ó ní àlááfíà ni pé: Dájúdájú fífi ọwọ́ pájú, lẹ́yìn píparí àdúà, kò bá ìlànà Ànábì mu, nítorí pé kò sì ẹ̀rí tí ó ní àlááfíà lórí rẹ̀.

Wọ́n bi Al-Imām Mālik – kí Ọlọ́hun kẹ́ ẹ – léèrè nípa ẹni tí ó máa ń fi àtẹ́lẹwọ́ rẹ̀ méjèèjì pá ojú rẹ̀ nígbà tí ó bá ń ṣe àdúà,  ó takò ó, ó sì sọ wí pé: “Mi ó mọ̀ ọ́n”. Wo: Kitābul-Witr, èyí tí Al-Marwazī kọ (ojú-ewé: 236).

Shaykhil-Islām – kí Ọlọ́hun kẹ́ ẹ – sọ wí pé: “Fífi ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì pá ojú rẹ̀, kò sí ẹrí fún un àyàfi Ḥadīth kan tàbí Ḥadīth méjì, èyí tí kò tó lò ní ẹ̀rí”  Wo: Al-Fatāwā (22/519).

 

brightness_1 Ó jẹ́ ohun tí ó bá Sunnah mu, kí ó jí ara ilé rẹ̀ láti jí dìde kírun lóru

Sunnah ni fún ọkùnrin kí ó jí ara ilé rẹ̀ fún ìrun òru. Bẹ́ẹ̀ náà ni obìnrin, Sunnah ni fún un kí ó jí ọkọ rẹ̀ àti gbogbo ara ilé rẹ̀ fún èyí. Èyí jẹ́ ara ríran ara ẹni lọ́wọ́ lórí dáadáa.

Ẹ̀rí rẹ̀ ni :

Ḥadīth tí ‘Ā’ishah – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá, ó sọ wí pé: “Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – máa kí gbogbo ìrun rẹ̀ lóru tán pátápátá, èmí sì máa ń dùbúlẹ̀ sí ààrin rẹ̀ àti Gábàsì. Tí ó bá wá fẹ́ kírun Witr, yóò jí mi, èmi náà yóò sì kírun Witr”. Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (512), Muslim sì gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (512).

Umm Salamah – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – sọ wí pé: “Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – jí lójú oorun, ó sì sọ wí pé: “Mímọ́ ni fún Ọlọ́hun, kín ni ohun tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ nínú àwọn pẹpẹ-ọ̀rọ̀, kín ni ohun tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ nínú àwọn àdánwò, tani yóò jí àwọn tí ń bẹ nínú yàrá dìde? – àwọn ìyàwó rẹ̀ ni ó gbà lérò – kí wọ́n le kírun, mélòómélòó obìnrin tí ó wọ aṣọ ní ayé, tí ó jẹ́ wí pé ìhòhò ni yóò wà ní ọjọ́ ìkẹyìn”  Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (6218).

 

brightness_1 Nínú Sunnah ni kí ẹni tí ó ń dìde kírun lóru ṣe ohun tí ó bá rọ̀ ọ́ lọ́rùn jùlọ

Nínú Sunnah ni kí ẹni tí ó ń dìde kírun lóru ṣe ohun tí ó bá rọ̀ ọ́ lọ́rùn jùlọ, nítorí kí ó má baà ṣe lapa lórí rírẹ ara ẹni nílẹ̀ fún Ọlọ́hun rẹ̀

Tí ó bá rẹ̀ ẹ́, yóò kírun ní ìjokòó

Nítorí Ḥadīth tí ’Anas – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá, ó sọ wí pé: “Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – wọ Mọṣáláṣí, okùn kan tí wọ́n fà gùn láàrin òpó méjì sì wà níbẹ̀, ní ó bá sọ wí pé: “Kín ni èyí?”. Wọ́n dá a lóhùn pé: Zaynab ló ni ín, ó ń kírun lọ́wọ́, tí òròjú bá bá a, tàbí ó rẹ̀ ẹ́, yóò dì í mú. Ó sì sọ wí pé: “Ẹ tú u, kí ẹni kẹ́ni nínú yín máa kírun nígbà tí ara rẹ̀ bá yá gágá, ṣùgbọ́n tí òròjú bá bá a, tàbí ó rẹ̀ ẹ́, kí ó jókòó”  Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (1150), Muslim sì gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (784).

– Tí òǹgbé bá ń ta á, yóò sùn, kí ó le dìde ní ẹni tí ara rẹ̀ yá gágá, yóò sì kírun lẹ́yìn èyí.

Nítorí Ḥadīth tí ‘Ā’ishah – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá pé: Dájúdájú Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – sọ wí pé: “Tí ẹni kẹ́ni nínú yín bá ń tòògbé lórí ìrun, kí ó sùn títí tí oorun yóò fi dá lójú rẹ̀. Nítorí pé dájúdájú ẹni kẹ́ni nínú yín tí ó bá ń kírun, nígbà tí ó ń tòògbé, le fẹ́ tọrọ àforíjìn, ṣùgbọ́n yóò máa bú ara rẹ̀”  Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (212), Muslim sì gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (786).

Bẹ́ẹ̀ náà ni tí òògbé, tàbí ohun tí ó jọ ọ́ bá ṣẹlẹ̀ sí i nígbà tí ó ń ké Al-Qur’ān lọ́wọ́ lóru, dájúdájú ohun tí ó jẹ́ Sunnah ni kí ó sùn, nítorí kí ó le lágbára.

Nítorí Ḥadīth tí Abū Hurayrah – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá pé: Dájúdájú Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – sọ wí pé: “ẹni kẹ́ni nínú yín bá dìde lóru, tí Al-Qur’ān tí ó ǹ ké wá ń lọ́ tìkọ̀ lórí ahọ́n rẹ̀, tí kò sì mọ ohun tí ó ń sọ mọ́, kí ó sùn padà” Muslim gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (787).

brightness_1 Ó jẹ́ Sunnah nígbà tí ó bá sálámà, níbi ìrun Witr rẹ̀, kí ó sọ wí pé:

Ó jẹ́ Sunnah nígbà tí ó bá sálámà, níbi ìrun Witr rẹ̀, kí ó sọ wí pé: (Subḥānal-Malikil-Quddūs {Mímọ́ ni fún Ọlọ́hun Ọba, Ẹni Mimọ́}) ní ẹ̀ẹ̀mẹta. Yóò gbé ohùn rẹ̀ sókè pẹ̀lú ẹ̀kẹta.

Ẹ̀rí rẹ̀ ni :

Ḥadīth tí ’Ubayy ọmọ Ka‘b – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá, ó sọ wí pé: “Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun  – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – máa ń ké níbi ìrun Witr {Sabbiḥisma Rabbikal-’A‘lā}, {Qul Yā ’ayyuhal-Kāfirūn} àti {Qul Huwallāhu ’Aḥd}, nígbà tí ó bá sálámà yóò sọ wí pé: Subḥānal-Malikil-Quddūs {Mímọ́ ni fún Ọlọ́hun Ọba, Ẹni Mimọ́, ní ẹ̀ẹ̀mẹta”  An-Nasā’ī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (1702), An-Nawawī àti Al-Albānī sì kà á sí ẹ̀gbàwá tí ó ní àlááfíà gẹ́gẹ́ bí ó ti síwájú láìpẹ́. Nínú Ḥadīth tí ‘Abdur-Raḥmān ọmọ Abzā – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá, ó wà níbẹ̀ pé: “Yóò gbé ohùn rẹ̀ sókè pẹ̀lú Subḥānal-Malikil-Quddūs {Mímọ́ ni fún Ọlọ́hun Ọba, Ẹni Mimọ́}) níbi ẹ̀kẹta” Aḥmad gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (15354), An-Nasā’ī pẹ̀lú òǹkà (1734), Al-Albānī sì kà á sí ẹ̀gbàwá tí ó ní àlááfíà (Taḥqīqu Mishkātil-Maṣābīḥ 1/398).