languageIcon
search
search
beforeFajronColorIcon Àwọn Sunnah tí kò ní àsìkò/ àwọn Sunnah àlùwàlá ni/ ( Iye òǹkà òpó-ìrun (rak‘ah) rẹ̀ 10 Àwọn Sunnah )
brightness_1 Pákò rínrìn

Èyí yóò wáyé síwájú kí a tó bẹ̀rẹ̀ àlùwàlá, tàbí síwájú kí a tó yọnu ṣùkùṣùkù. Èyí ni ààyè kejì, èyí tí rínrin pákò jẹ́ Sunnah níbẹ̀ –ààyè àkọ́kọ́ ti siwájú-. Nítorí náà ó jẹ́ ohun tí a fẹ́, nínú ẹ̀sìn Islām, fún ẹni tí ó bá fẹ́ ṣe àlùwàlá, kí ó rin pákò. Nítorí Ḥadīth tí Abū Hurayrah – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá pé; dájúdájú Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – sọ wí pé: “Tí kì í bá ṣe wí pé nítorí kí n má kó ìnira bá ìjọ mi ni, dájúdájá mi ò bá pa wọ́n láṣẹ kí wọ́n máa rin pákò, ní gbogbo ìgbà tí wọ́n bá fẹ́ ṣe àlùwàlá”. Aḥmad gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (9928), Ibn Khuzaymah sì gbà á wá, ó sì kà á sí ẹ̀gbàwá tí ó ní àlááfíà (1/73/140), Al-Ḥākim (1/245), Al-Bukhārī  gbà á wá, láìdárúkọ gbogbo àwọn tí ó gbá á lọ́wọ́ ara wọn, pẹ̀lú ẹ̀rọ-ọ̀rọ̀ tí ó túmọ̀ sí pé ó dájú, níbi àkòrí yìí: Ọ̀rọ̀ nípa rínrin pákò tútù àti gbígbẹ̀ fún aláàwẹ̀.

Àti nítorí Ḥadīth tí  ‘Ā’ishah –kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá, ó sọ wí pé: “A máa ń bá a (Ànábì) pèsè pákò rẹ̀ àti omi tí yóò fi ṣe ìmọ́ra sílẹ̀. Ọlọ́hun sì máa ń ta á jí, nígbà tí Ó bá fẹ́ láti ta á jí ní òru, yóò sì rin pákò, yóò ṣe àlùwàlá, yóò sì kírun”  Muslim gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (746).

brightness_1 Fífọ àwọn oríkèé tí a máa ń fọ̀ níbi àlùwàlá ní ẹ̀ẹ̀mẹta, ẹ̀ẹ̀mẹta

Ọ̀ranyàn ni fífọ̀ àkọ́kọ́, ṣùgbọ́n ìkejì àti ìkẹta jẹ́ Sunnah. A kò sì gbọdọ̀ lé e kún ju ẹ̀ẹ̀mẹta lọ.

Ẹ̀rí rẹ̀ ni :

Ohun tí ó fi ẹ̀sẹ̀ rinlẹ̀ ní ọ̀dọ̀ Al-Bukhārī  – kí Ọlọ́hun kẹ́ ẹ – nínú Ḥadīth Ibn ‘Abbās – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí àwọn méjèèjì – gbà wá, èyí tí Al-Bukhārī  àti Muslim panupọ̀ gbà wá pé: “Dájúdájú Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – ṣe àlùwàlá ní ẹ̀ẹ̀kan ẹ̀ẹ̀kan” Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (157). Ó tún fi ẹ̀sẹ̀ rinlẹ̀, ní ọ̀dọ̀ Al-Bukhārī bákan náa, nínú Ḥadīth tí ‘Abdullāh ọmọ Zayd – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá pé: “Dájúdájú Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – ṣe àlùwàlá ní ẹ̀ẹ̀mejì ẹ̀ẹ̀méjì” Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (158). Ó tún fi ẹ̀sẹ̀ rinlẹ̀, nínú Ṣaḥīḥu méjèèjì, nínú adīth tí ‘Uthmān – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i- gbà wá pé: “Dájúdájú Ànábì -kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – ṣe àlùwàlá ní ẹ̀ẹ̀mẹta ẹ̀ẹ̀mẹta” Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (159). Fún ìdí èyí, nínú ohun tí ó ní ọlá jùlọ ni mímáa ṣe é ní oníraǹran ní ẹ̀ẹ̀kọ̀ọ̀kan, kí ó ṣe é ní ẹ̀ẹ̀kọ̀ọ̀kan nígbà kan, ẹ̀ẹ̀mejì ẹ̀ẹ̀mejì nígbà mìíràn tàbí ẹ̀ẹ̀mẹta ẹ̀ẹ̀mẹta nígbà mìíràn, tàbí kí ó ṣe é pẹ̀lú òǹkà ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ nígbà mìíràn. Ní àpèjúwe, kí ó fọ ojú ní ẹ̀ẹ̀mẹta ẹ̀ẹ̀mẹta, ọwọ́ méjèèjì ní ẹ̀ẹ̀mejì ẹ̀ẹ̀mejì, gìgísẹ̀ méjèèjì ní ẹ̀ẹ̀kọ̀ọ̀kan, gẹ́gẹ́ bí ó ti wà nínú Ṣaḥīḥu méjèèjì, nínú adīth tí ‘Abdullāh ọmọ Zayd –kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i- gbà wá nínú ẹ̀gbàwá mìíràn. Wo: Zādul-Ma‘ād (1/192). Ṣùgbọ́n ohun tí ó gbajúmọ̀ jùlọ ni kí ó ṣe é pé ní ẹ̀ẹ̀mẹta ẹ̀ẹ̀mẹta, èyí ni ìlànà Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a –.

 

brightness_1 Àdúà tí a máa ń ṣe lẹ́yìn àlùwàlá

‘Umar –kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i- sọ wí pé: Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – sọ wí pé: “Kò sí ẹnìkankan nínú yín, tí yóò ṣe àlùwàlá, tí yóò sì ṣe àlùwàlá náà dé ògóńgó - tí yóò ṣe é dáadáa-, lẹ́yìn náà tí yóò sọ wí pé: ’Ashhadu ’an lā ’ilāha ’illallāh, wa’anna Muḥammadan ‘abduhu warasūluh  (Mo jẹ́rìí pé kò sí ọlọ́hun kankan tí ó lẹ́tọ̀ọ́ sí ìjọsìn àyàfi Ọlọ́hun Allāh nìkan, àti pé Òjíṣẹ́ Ọlọ́hun Muḥammad, níti pàápàá, jẹ́ ẹrúsìn Rẹ̀ àti Ìránṣẹ́ Rẹ̀), àyàfi kí wọ́n ṣí àwọn ìlẹ̀kùn ọgbà-ìdẹ̀ra Al-Jannah mẹ́jọ̀ọ̀jọ̀ sílẹ̀ fún un, yóò wọlé láti ibi èyí tí ó bá fẹ́ nínú rẹ̀” Muslim gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (234).

Tàbí: Ohun tí  ó wá nínú Ḥadīth tí Abū Sa‘īd – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá, tí ó ṣe àfitì rẹ̀ sí Ànábì pé: “Ẹni kẹ́ni  tí ó bá ṣe àlùwàlá, tí ó parí àlùwàlá rẹ̀, tí ó sì wí pé: Subḥānakallāhumma wabiḥamdika ’ashhadu ’an lā ilāha illā ’Anta astaghfiruka wa’atūbu ’ilayk (Mímọ́ ni fún Ọ, Ìrẹ Ọlọ́hun, mo tún ṣe ọpẹ́ àti ẹyìn fún Ọ; mo jẹ́rìí pé kò sí ọlọ́hun kankan tó lẹ́tọ̀ọ́ sí ìjọsìn àyàfi Ìwọ nìkan. Mò ń tọrọ àforíjìn Rẹ̀, mo sì ronúpìwàdà lọ sí ọ̀dọ̀ Rẹ̀), Ọlọ́hun yóò fi òǹtẹ̀ tẹ̀ ẹ́ (ṭāba‘u tàbí ṭābi‘u jẹ́ èdè Lárúbáwá méjì tí ó já geere, ohun ni wọ́n tún máa ń pè ní khātim (òǹtẹ̀) nínú èdè Lárúbáwá, ìtumọ̀ ṭaba‘a ni: Ó fi òǹtẹ̀ tẹ̀ ẹ́), lẹ́yìn náà wọ́n yóò gbé e lọ sókè ní abẹ́ Ìtẹ́-Ọlá Ọlọ́hun, wọn kò sì ní kán an títí di ọjọ́ Ìgbéǹde”  An-Nasā’ī gbà á wá nínú ‘Amalul-Yawmi wal-Laylah (ojú-ewé147), Al-Ḥākim náà gbà á wá (1/246). Ibn Ḥajar – kí Ọlọ́hun kẹ́ ẹ – ka ojúpọ̀nà tí ó gbà wá sí èyí tí ó ní àlááfíà, wo: Natā’ijul-’Afkār (1/246). Ó tún ṣàlàyé pé kò ní àlááfíà dé ọ̀dọ̀ Ànábì, a jẹ́ wí pé ọ̀rọ̀ sàábé ni. Èyí kò le kó ìpalára bá a, nítorí pé dájúdájú ó ní ìdájọ́ ohun tí wọ́n fi tì sí Ànábì, nítorí pé ara ohun tí a kò le fi làákàyè lásán gbé kalẹ̀ ni.