languageIcon
search
search
beforeFajronColorIcon Àwọn Sunnah tó ní àsìkò/ Àsìkò ìrun àṣálẹ́/ ( Iye òǹkà òpó-ìrun (rak‘ah) rẹ̀ 4 Àwọn Sunnah )
brightness_1 Nínú Sunnah ni kí á kọ̀ fún àwọn ọmọdé láti máa jáde ní ìbẹ̀rẹ̀ àsìkò ìrun àṣálẹ́

Ìṣọ́ kúrò lọ́wọ́ àwọn èṣù àti àlùjànǹnú wà níbi lílo ẹ̀kọ́ méjèèjì yìí. Níbi kíkọ̀ fún àwọn ọmọdé láti jáde ní ìbẹ̀rẹ̀ àsìkò ìrun àṣálẹ̀, ìṣọ́ wà níbẹ̀ fún wọn lọ́wọ́ àwọn èṣù, èyí tó máa ń fọ́n jáde ní àsìkò yìí. bẹ́ẹ̀ náà ni títi ìlẹ̀kùn ní àsìkò yìí àti dídárúkọ Ọlọ́hun – Ọba tí Ọlá Rẹ̀ ga –nígbà tí a bá fẹ́ tì í. Mélòó mélòó ọmọdé àti ilé ní àwọn èṣù ti ní ìkápá lórí rẹ̀ ní àsìkò yìí, kín ni ó tún wá tóbi tó bí ẹ̀sìn Islām ti ṣọ́ àwọn ọmọdé wa àti ilé wa!

Ẹ̀rí rẹ̀ ni :

Ḥadīth tí Jābir ọmọ ‘Abdil-Lāh – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí àwọn méjèèjì – gbà wá, ó sọ wí pé: Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – sọ wí pé: “Nígbà tí òru bá ru batakun – tàbí nígbà tí ẹ bá di ìrọ̀lẹ̀ –, ẹ kó àwọn ọmọdé yín ró sínú ilé, nítorí pé dájúdájú àwọn èṣù máa ń fọ́nká nígbà náà, tí wákàtí kan bá ti bọ́ sẹ́yìn nínú òru, ẹ tú wọn sílẹ̀, ẹ sì ti àwọn ìlẹ̀kùn, ẹ sì dárúkọ́ Ọlọ́hun sí i, nítorí pé dájúdájú èṣù kò le ṣí ìlẹ̀kùn kankan tí wọ́n tì pa”. Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (3304), Muslim sì gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (2012). Ìtumọ̀ junḥul-layl ni: Bíbẹ̀rẹ̀ òru lẹ́yìn tí òòrùn bá ti wọ̀.

Kíkọ̀ fún àwọn ọmọdé láti jáde àti títi ìlẹ̀kùn ní ìbẹ̀rẹ̀ àsìkò ìrun àṣálẹ̀, jẹ́ ohun tí a fẹ́ (kì í ṣe ọ̀ranyàn). Wo: àwọn àlàyé ìdájọ́ ẹ̀sìn ti ìgbìmọ̀ gbére (26/316).

 

brightness_1 Nínú Sunnah ni kí á ti àwọn ìlẹ̀kùn pa ní ìbẹ̀rẹ̀ àsìkò ìrun àṣálẹ́, kí á sì dárúkọ Ọlọ́hun, Ọba tí Ọlá Rẹ̀ ga, nígbà náà

Ìṣọ́ kúrò lọ́wọ́ àwọn èṣù àti àlùjànǹnú wà níbi lílo ẹ̀kọ́ méjèèjì yìí. Níbi kíkọ̀ fún àwọn ọmọdé láti jáde ní ìbẹ̀rẹ̀ àsìkò ìrun àṣálẹ̀, ìṣọ́ wà níbẹ̀ fún wọn lọ́wọ́ àwọn èṣù, èyí tó máa ń fọ́n jáde ní àsìkò yìí. bẹ́ẹ̀ náà ni títi ìlẹ̀kùn ní àsìkò yìí àti dídárúkọ Ọlọ́hun – Ọba tí Ọlá Rẹ̀ ga –nígbà tí a bá fẹ́ tì í. Mélòó mélòó ọmọdé àti ilé ní àwọn èṣù ti ní ìkápá lórí rẹ̀ ní àsìkò yìí, kín ni ó tún wá tóbi tó bí ẹ̀sìn Islām ti ṣọ́ àwọn ọmọdé wa àti ilé wa!

Ẹ̀rí rẹ̀ ni :

Ḥadīth tí Jābir ọmọ ‘Abdil-Lāh – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí àwọn méjèèjì – gbà wá, ó sọ wí pé: Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – sọ wí pé: “Nígbà tí òru bá ru batakun – tàbí nígbà tí ẹ bá di ìrọ̀lẹ̀ –, ẹ kó àwọn ọmọdé yín ró sínú ilé, nítorí pé dájúdájú àwọn èṣù máa ń fọ́nká nígbà náà, tí wákàtí kan bá ti bọ́ sẹ́yìn nínú òru, ẹ tú wọn sílẹ̀, ẹ sì ti àwọn ìlẹ̀kùn, ẹ sì dárúkọ́ Ọlọ́hun sí i, nítorí pé dájúdájú èṣù kò le ṣí ìlẹ̀kùn kankan tí wọ́n tì pa”. Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (3304), Muslim sì gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (2012). Ìtumọ̀ junḥul-layl ni: Bíbẹ̀rẹ̀ òru lẹ́yìn tí òòrùn bá ti wọ̀.

Kíkọ̀ fún àwọn ọmọdé láti jáde àti títi ìlẹ̀kùn ní ìbẹ̀rẹ̀ àsìkò ìrun àṣálẹ̀, jẹ́ ohun tí a fẹ́ (kì í ṣe ọ̀ranyàn). Wo: àwọn àlàyé ìdájọ́ ẹ̀sìn ti ìgbìmọ̀ gbére (26/316).

brightness_1 Kíkí òpó-ìrun méjì síwájú ìrun àṣálẹ́

Nítorí Hadīth tí ‘Abdullāh ọmọ Mughaffal Al-Muzanī – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá, láti ọ̀dọ̀ Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a –, pé ó sọ wí pé: “Ẹ máa kírun síwájú ìrun àṣálẹ́”, ó sọ ní ẹ̀ẹ̀kẹta pé: Fún ẹni tó bá fẹ́, nítorí pé ó kórìíra kí àwọn èèyàn mú un (ní ìlànà tí wọn kò ní fi sílẹ̀)”. Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (1183).

Bákan náà wọ́n ṣe kíkí òpó-ìrun méjì, láàrin pípe ìrun àti gbígbé ìrun dìde, ní Sunnah

Bóyá òpó-ìrun méjèèjì yìí jẹ́ èyí tí a máa ń kí síwájú tàbí lẹ́yìn ìrun ọ̀ranyàn bíi èyí tí a máa ń kí síwájú ìrun àárọ̀ àti ọ̀sán, dájúdájú ìrun àkígbọrẹ tí a máa ń kí síwájú tàbí lẹ́yìn ìrun, tí ó bá kí i, yóò tó o kúrò níbi òpó-ìrun méjèèjì yìí. Ṣùgbọ́n tí ó bá jẹ́ wí pé ó jókòó sí Mọṣáláṣí, lẹ́yìn náà tí apèrun wá pèrun fún ìrun ìrọ̀lẹ̀ tàbí ìrun alẹ́, dájúdájú nínú Sunnah ni kí ó dìde, kí ó sì kí òpó-ìrun méjì.

Ẹ̀rí rẹ̀ ni :

Hadīth tí ‘Abdullāh ọmọ Mughaffal Al-Muzanī – kí Ọlọ́hun yọ́nú sí i – gbà wá, ó sọ wí pé: Ìránṣẹ́ Ọlọ́hun – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a –, sọ wí pé: “Ìrun ń bẹ láàrin pípe ìrun àti gbígbé ìrun dìde”, ó sọ ọ́ ní ẹ̀ẹ̀mẹta, ó sọ níbi ìkẹta pé: “Fún ẹni tó bá fẹ́”. Al-Bukhārī gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (624), Muslim gbà á wá pẹ̀lú òǹkà (838).

Kò sí ìyeméjì níbi pé dájúdájú kíkí òpó-ìrun méjì síwájú ìrun àṣálẹ̀ tàbí láàrin pípe ìrun àti gbígbé ìrun dìde, kì í ṣe ohun tó kanpá bíi kíkanpá àwọn ìrun àkígbọrẹ tí a máa ń kí síwájú tàbí lẹ́yìn ìrun ọ̀ranyàn, ṣùgbọ́n a máa ń pa á tì ní ẹ̀ẹ́kọ̀ọ̀kan. Ìdí níyí, tí Ànábì – kí ìkẹ́ àti ọlà Ọlọ́hun máa bá a – fi sọ níbi ẹ̀ẹ̀kẹta pé: “Fún ẹni tó bá fẹ́”, nítorí pé ó kórìíra kí àwọn èèyàn mú un (tí ìlànà tí wọn kò fi sílẹ̀).